ترجمة سورة الليل

الترجمة اليورباوية

ترجمة معاني سورة الليل باللغة اليورباوية من كتاب الترجمة اليورباوية.
من تأليف: أبو رحيمة ميكائيل أيكوييني .

(Allāhu) búra pẹ̀lú alẹ́ nígbà tí (ilẹ̀) bá ṣú.
Ó tún búra pẹ̀lú ọ̀sán nígbà tí (ọ̀sán) bá pọ́n.
Ó tún búra pẹ̀lú Ẹni tí Ó dá akọ àti abo.
____________________
Allāhu (subhānahu wa ta'ālā) ni Ẹni tí Ó dá akọ àti abo. Ó sì ń fi ara Rẹ̀ búra.
Dájúdájú iṣẹ́ yín, ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ni.
Ní ti ẹni tí ó bá tọrẹ, tí ó sì bẹ̀rù (Allāhu),
(tí) ó tún pe ẹ̀san rere ní òdodo,
A sì máa ṣe iṣẹ́ rere ní ìrọ̀rùn fún un.
Ní ti ẹni tí ó bá yahun, tí ó sì rí ara rẹ̀ lẹ́ni t’ó rọrọ̀ tayọ ẹ̀san ọ̀run,
(tí) ó tún pe ẹ̀san rere ní irọ́,
A sì máa ṣe iṣẹ́ aburú ní ìrọ̀rùn fún un.
Dúkìá rẹ̀ kò sì níí rọ̀ ọ́ lọ́rọ̀ nígbà tí ó bá já bọ́ (sínú Iná).
Dájúdájú tiWa ni (láti ṣàlàyé) ìmọ̀nà.
Àti pé dájúdájú tiWa ni ọ̀run àti ayé.
Nítorí náà, Mo ti fi Iná eléjò fòfò kìlọ̀ fun yín.
Kò sí ẹni tí ó máa wọ inú rẹ̀ àfi olórí burúkú,
ẹni tí ó pe òdodo nírọ́, tí ó sì kẹ̀yìn sí i.
Wọ́n sì máa gbé (Iná) jìnnà sí olùbẹ̀rù (Allāhu),
ẹni t’ó ń fi dúkìá rẹ̀ tọrẹ, tí ó ń ṣàfọ̀mọ́ (rẹ̀).
Kò sì sí oore ìdẹ̀ra kan tí (ó ní lọ́kàn) láti gbà ní ẹ̀san ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni,
bí kò ṣe pé láti fi wá ojú rere Olúwa rẹ̀, Ẹni Gíga jùlọ.
Láìpẹ́ ó sì máa yọ́nú (sí ẹ̀san rẹ̀).
سورة الليل
معلومات السورة
الكتب
الفتاوى
الأقوال
التفسيرات

سورة (اللَّيل) مكية، نزلت بعد سورة (الأعلى)، وقد افتُتحت بقَسَم الله عز وجل بـ(اللَّيل)، وهو آيةٌ من آيات الله الدالةِ على عظمته وقُدْرته وتصرُّفه في هذا الكون، وبيَّنت السورة الكريمة تبايُنَ مَساعي البشر، المؤديَ إلى تبايُنِ مستقرَّاتهم في الدار الآخرة، وفي ذلك دعوةٌ إلى السعيِ إلى الخير، وتركِ الشر.

ترتيبها المصحفي
92
نوعها
مكية
ألفاظها
71
ترتيب نزولها
9
العد المدني الأول
21
العد المدني الأخير
21
العد البصري
21
العد الكوفي
21
العد الشامي
21

* سورة (اللَّيل):

سُمِّيت سورة (اللَّيل) بهذا الاسم؛ لافتتاحها بقَسَمِ الله عز وجل بـ(اللَّيل).

1. القَسَم على تبايُنِ سعي البشر (١-٤).

2. اعملوا فكلٌّ مُيسَّر (٥-١٣).

3. إنذار وتحذير (١٤- ٢١).

ينظر: "التفسير الموضوعي لسور القرآن الكريم" لمجموعة من العلماء (9/172).

بيانُ قدرة الله عزَّ وجلَّ، وتصرُّفِه في هذا الكون، وتبايُنِ سعيِ البشر المؤدي إلى تباين مآلاتهم.

ينظر: "التحرير والتنوير" لابن عاشور (30 /378).